Ní orílẹ̀ èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá (Democratic Republic of the Yorùbá D.R.Y), à ò ní sọ èdè ẹrú, èdè Yorùbá pọ́ńbélé ni a óò máa sọ bẹ́ẹ̀ sì ni kíkọsílẹ̀ rẹ̀ gbọ́dọ̀ ni àwọn àmì tó yẹ lórí tàbí nìdí álífábẹ́ẹ́tì kọ̀ọ̀kan èyí yóò mú kó rọrùn fún òǹkàwé láti pe ọ̀rọ̀ náà bí ó ti yẹ.

Ìdí ni pé, àwọn ọ̀rọ̀ kan wà nínú èdè Yorùbá tó jẹ́ pé bákan náà ni kíkọsílẹ̀ wọn ṣùgbọ́n ìtumọ̀ wọn yàtọ̀. Bí àpẹẹrẹ odó, odò. Odó ni ohun èlò nínú ilé tí a fi ń gún iyán. Omi tó ń ṣàn ni odò. 

Ọkọ́, oko, ọkọ̀. Ọkọ́ ni ọkàn lára ohun èlò fún iṣẹ́ ọ̀gbìn, oko ni ibi tí àwọn àgbẹ̀ ti ń ṣiṣẹ́ láti rí oúnjẹ, ohun ìrìnnà ni ọkọ̀. 

Tí a bá wo àwọn ọ̀rọ̀ yí, a óò ríi wípé bákan náà ni kíkọsílẹ̀ wọn ṣùgbọ́n àmì tí a fi sórí àti ìdí wọn ló gbé ìyàtọ̀ wọn jáde, ìdí nìyí tí a fi gbọdọ ri dájú pé a ò fi ojú pa àwọn àmì wọ̀nyí rẹ̀ nítorí ó ṣe pàtàkì púpọ̀ nínú èdè Yorùbá.

A dúpẹ́ lọ́wọ́ Olódùmarè tó gbé màmá wa ìyá ààfin Modupẹọla Onitiri-Abiọla dìde ní déédéé ìgbà yí àti ní déédéé àsìkò yí láti dá ògo ìran Yorùbá tó ti sọnù padà, nítorí màmá wa MOA ti sọ fún wa pé àlàkalẹ̀ ètò ìsèjọba tí Olódùmarè fún wọn yóò dá wa padà sí orírun wa ni. A kí gbogbo àwa ọmọ Aládé pé a kú oríire!

The Democratic Republic of the Yoruba also known in the Yoruba history as Yoruba Nation, Yoruba Kingdom, Yoruba Land and Yoruba Country is the newest nation in the world. The 55th nation in Africa and 17th in Western Africa as of 12th April 2024. Yoruba is know a sovereign nation and its no longer part of Nigeria.